1 Chronicles 16:8-22

8 aẸ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀,
ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
9Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i,
Ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀
10Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́;
jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
11Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀;
E wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.

12Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe,
iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
13A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀,
àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
14Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa;
ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.

15Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé,
ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹgbẹ̀rún ìran,
16májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu,
ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
17Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu,
gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
18“Sí ọ, ni Èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani.
Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”

19Nígbà tí wọn kéré ní iye,
wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
20wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè
láti ìjọba kan sí èkejì.
21Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú;
nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
22“Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni ààmì òróró mi;
Má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”
Copyright information for YorBMYO